Àwọn ètò kíkà ọ̀fé àti àyọkà tó ní ṣe pẹ̀lú Owe 3:5

Ìyípadà Láti Ṣẹ́pá Àwọn Ìdààmú Ọkàn
Ọjọ́ Mẹ́ta
Ti ayé rẹ̀ bá yàtọ̀ sí ètò Ọlọ́run, dandan ni kí o kọjú ìṣòro àti ìdààmú. Ti ẹ̀dùn ọkàn bá borí ẹ, tó bẹ̀rẹ̀ sì ni nípa lórí àlàáfíà rẹ, wàá ri pe o ti tì ra re sínú àhámọ́ tó ṣòro láti jade kuro. O nilo láti wá iwọntunwọnsi ki o si gbẹkẹle Ọlọ́run. Je ki Tony Evans salaye bó o ṣe lè lómìnira ọkàn.

Líla Ìgbà Ìṣòro Kọjá
Ọjọ́ Mẹ́rin
A kò lè fẹ́ àwọn ìdojúkọ kù nínú ayé wa. Ṣùgbọ́n nínú Ètò kúkúrú ọlọ́jọ́-4 yìí, a ó máa gbà wá ní ìyànjú láti mọ̀ pé a kò dá nìkan wà, pé Ọlọ́run ní ète fún ìrora wa, àti pé yíó lò ó fún ètò gíga Rẹ̀.

ỌLỌ́RUN + ÌLÉPA: Ọ̀nà Láti Gbé Ìlépa Kalẹ̀ Gẹ́gẹ́ Bí Kristẹni
Ojọ́ Márùn-ún
Ǹjẹ́ o dára láti ní ìlépa gégé bí Kristẹni? Báwo ní o ṣe lẹ̀ mọ̀ tí ìlépa rẹ bá wá látọ̀dọ̀ Ọlọ́run tàbí ara rẹ? Àti wípé báwo ni ìlépa Kristẹni ṣe rí ní pàtó? Nínú ètò kíkà ọlọ́jọ́ márùn-ún yìí, o máa ṣàwárí nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run láti rí ìtọ́sọ́nà lórí gbígbé ìlépa tó kún fún ore-ọ̀fẹ́ kalẹ̀!

Ṣíṣe Àkóso Àkókò N'ìlànà Ọlọ́run
Ọjọ́ mẹ́fà
Bá a ṣe máa ń lo àkókò wa lọ́nà tó bófin mu lè fa másùnmáwo nígbà tá a bá ń sapá láti "ṣàkóso" ìgbésí ayé wa nípasẹ̀ agbára àti ìkóra-ẹni-níjàánu. Ṣùgbọ́n Bíbélì sọ fún wa pé a máa ń ní àlàáfíà àti ìsinmi nígbà tá a bá gbẹ́kẹ̀ lé Ọlọ́run nípa àkókò wa. Nínú ìwéwèé ọjọ́ mẹ́fà yìí, wàá mọ bí ọ̀nà tí Ọlọ́run gbà ń lo àkókò rẹ ṣe lè mú kó o rí gbogbo ohun rere tó ní fún ọ gbà, títí kan ayọ̀ àti àlàáfíà Rẹ̀.

Ìràpadà Ìlépa-Ọkàn
Ọjọ́ Méje
Kíni a lè ṣe nígbà tí àwọn ìlépa wa bá dàbí èyí tó jìnà réré tàbí bíi ìgbà tí a kò bá lè bá a láíláí? Lẹ́yìn tí mo borí ìlòkulò àti ìbanilọ́kànjẹ́, pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn ti ìkọ̀sílẹ̀, mo ti dojúkọ ìbéèrè yìí lẹ́ẹ̀kànsi. Bóyá ò ń ní ìpèníjà ti àjálù tàbí ọ̀fọ̀, tàbí ìbànújẹ́ ti àkókò ìdádúró, ìlépa Ọlọ́run fún ìgbésí-ayé rẹ ṣì wà láàyè! Ọ̀rẹ́, àkókò tó láti lá àlá lẹ́ẹ̀kansi.

Jesu fẹràn mi
Ọjọ́ Méje
Tí ẹnìkan bá béèrè lọ́wọ́ rẹ pé, “Kí nì mo ní láti gbàgbọ láti lè jẹ́ Kristẹni?” Kí nì ó sọ? Olùṣọ́-àgùntàn tó jẹ akọròyìn tẹ́lẹ̀ lo ọ̀rọ̀ orin, “Jésù Fẹ Mi Mo Mọ Bẹ́ẹ̀, Bíbélì L’o Sọ Fún Mi” láti jẹ́ kí ìgbàgbọ yé ọ. Akọ̀wé John S. Dickerson ṣàlàyé àwọn ìgbàgbọ ti Kristẹni àti ìdí tí wọ́n ṣe pàtàkì.

Wá Ọlọ́run Láàrin Rẹ̀
Ojó Méwàá
Ìrẹ̀wẹ̀sì. Àníyàn. Àwọn okùnfà àti àwọn ìṣẹ̀lẹ̀ tí ó ro ni lára máa ń ní ipa tí ó ní agbára lórí ọpọlọ, ìmọ̀lára àtì ìgbé-ayé ẹ̀mí wa. Ní àwọn àkókò yìí, wíwá Ọlọ́run á dàbíi pé ó ṣòro tí kò sì já mọ́ ǹǹkan kan. Èròńgbà ètò kíkà yìí, "Wíwá Ọlọ́run Láàrin Rẹ̀" ni láti gbà ọ́ ní ìyànjú àti láti kọ́ ọ ní ọ̀nà tí o fi lè ṣe ìtara níwájú Ọlọ́run, kí o ba lè ní àlàáfíà Ọlọ́run nínú irú ipòkípò tí o lè wà.