Àwọn ètò kíkà ọ̀fé àti àyọkà tó ní ṣe pẹ̀lú Filp 1:28

Nínú Ohun Gbogbo
Ọjọ́ Márùn-ún
Ìwé náà tí Pọ́ọ̀lù kọ sí ìjọ tó wà ní Fílípì ló ti la ìran kan kọjá sí ìmí láti mú ìtùnú àti ìpèníjà bá ọkàn wa lónìí. Ètò kíkà ọlọ́jọ́ márùn-ún yìí yóò fún ọ ní ìtọ́wọ̀ ìwé Fílípì, lẹ́yìn ọgọ́rùn-ún mélòó kan ọdún tí Ọlọ́run ti t'ọwọ́ Pọ́ọ̀lù kọ ọ́. Kí Ọlọ́run kún ọ fún ìyanu àti ìfojúsọ́nà bí o ti ń ka ìwé tó kún fún ayọ̀ yí! Nítorí àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí kìí ṣe ti Pọ́ọ̀lù nìkan sí ìjọ àtijọ́ kan—ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sí ọ ni wọ́n jẹ́.

Ẹ̀jẹ́ Náà
Ọjọ́ mẹ́fà
Nínú Ètò Bíbélì Life.Church yí, àwọn l'ọkọ l'áya (tọkọtaya) mẹ́fà kọ nípa májẹ̀mú ìgbéyàwó tí wọn kò ní àǹfààní láti kà níwájú pẹpẹ. Àwọn májẹ̀mú ìpalémọ, oun-tó-ṣe-pàtàkì, ìlépa, àjọṣepọ̀, àìlábàwón, àdúrà ni májẹ̀mú tí ó máa ń mú ìgbéyàwó lọ létòletò kọjá àkókò adùn ayẹyẹ ìgbéyàwó. Bóyá o ti gbéyàwó tàbí o kò ì tí gbéyàwó, àkókò ti tó láti dá májẹ̀mú

Ìgboyà
Ọ̀sẹ̀ kan
Kọ́ ohun tí Bíbélì sọ nípa ìgboyà. Ètò kíkà “Ìgboyà” rán àwọn onígbàgbọ́ létí ẹni tí wọ́n jẹ́ nínú Kristi àti nínú ìjọba Ọlọ́run. Nígbà tí a bá jẹ́ ti Ọlọrun, a ní òmìnira láti súnmọ́-On tààrà. Kà lẹ́ẹ̀kansi - tàbí bóyá fún ìgbà àkọ́kọ́ - àwọn ìdánilójú pé ipò rẹ nínú ìdílé Ọlọrun wà síbẹ̀.