Àwọn ètò kíkà ọ̀fé àti àyọkà tó ní ṣe pẹ̀lú Mat 22:37

Iṣé Ìrànṣe Ìtayọ
Ojo meta
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ìdí tí ó l'ẹ́sẹ̀ nílẹ̀ ni ó wà tí a fi gbọ́dọ̀ lépa ìtayọ ní ẹnú iṣẹ́ wa: Ìtayọ ń mú iṣẹ́ wa gbòòrò sí, ó ń jẹ́ kí a ní ipa rere, ó sì lè y'ọrí sí àǹfààní láti tan ìhìnrere ká. Ṣùgbọ́n bí a ó ti rí i nínú ètò ọlọ́jọ́ mẹ́ta yìí, a ní láti lépa ìtayọ fún ìdì pàtàkì kan—nítorí pé ìtayọ ni ọ̀nà tí a fi lè fi àbùdá Ọlọ́run hàn, kí a sì ní ìfẹ́ àti kí a ṣiṣẹ́ sìn ọmọlàkejì wa bíi ara wa nípa iṣẹ́ tí a yàn láàyò.

Fẹ́ràn kí o sì máa Fẹ́ràn Síwájú síi
Ọjọ́ 3
Ṣíṣe ayẹyẹ ìfẹ́ kọja ṣíṣe-é ní ọjọ́ kan pato; ó jẹ́ ìgbésí ayé tí ń rán àwọn ẹlòmíràn létí ní ìgbà gbogbo pé ìfẹ́ Ọlọ́run wá láti mú wa ní ara dá, mú wa padà bọ̀ sípò, àti láti fún wa ní ìyè tí ń p'òkìkí oore rẹ̀. Mo pè ọ́ láti ka ètò ẹ̀kọ́ ọlọ́jọ́ mẹ́ta l'órí ohun tí ifẹ í ṣe àti ohun tí ó jọ l'áti ní ìfẹ́ àwọn ẹlòmíràn bí Ọlọ́run ṣe fẹ́ kí á ṣe.

ỌLỌ́RUN + ÌLÉPA: Ọ̀nà Láti Gbé Ìlépa Kalẹ̀ Gẹ́gẹ́ Bí Kristẹni
Ojọ́ Márùn-ún
Ǹjẹ́ o dára láti ní ìlépa gégé bí Kristẹni? Báwo ní o ṣe lẹ̀ mọ̀ tí ìlépa rẹ bá wá látọ̀dọ̀ Ọlọ́run tàbí ara rẹ? Àti wípé báwo ni ìlépa Kristẹni ṣe rí ní pàtó? Nínú ètò kíkà ọlọ́jọ́ márùn-ún yìí, o máa ṣàwárí nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run láti rí ìtọ́sọ́nà lórí gbígbé ìlépa tó kún fún ore-ọ̀fẹ́ kalẹ̀!

Dídàgbà Nínú Ìfẹ́
Ọjọ́ 5
Ohun tí ó ṣe pàtàkí ní pàtó ní fífẹ́ Ọlọ́run àti fífẹ́ ọmọlàkejì, ṣùgbọ́n báwo ni a ó ṣe ṣe èyí dé ojú àmì? Òtítọ́ ibẹ̀ ni wípé, a kò lè ní ìfẹ́ ẹlòmíràn dunjú nínú agbára ti ara wa. Ṣùgbọ́n nígbàtí a bá gbé ojú s'ókè sí Ọlọ́run tí a rẹ ara wa s'ílẹ̀ ní ìrẹ̀lẹ̀, a lè gbé ayé láti inú ògidì ìfẹ́ Ọlọ́run tí ó ní agbára. Kọ́ síi nípa dídàgbà nínú ìfẹ́ nínú Ètò-ẹ̀kọ́ Bíbélì ọlọ́jọ́-5 láti ọwọ́ Olùṣọ́-àgùntàn Amy Groeschel.

Ṣíṣe Àkóso Àkókò N'ìlànà Ọlọ́run
Ọjọ́ mẹ́fà
Bá a ṣe máa ń lo àkókò wa lọ́nà tó bófin mu lè fa másùnmáwo nígbà tá a bá ń sapá láti "ṣàkóso" ìgbésí ayé wa nípasẹ̀ agbára àti ìkóra-ẹni-níjàánu. Ṣùgbọ́n Bíbélì sọ fún wa pé a máa ń ní àlàáfíà àti ìsinmi nígbà tá a bá gbẹ́kẹ̀ lé Ọlọ́run nípa àkókò wa. Nínú ìwéwèé ọjọ́ mẹ́fà yìí, wàá mọ bí ọ̀nà tí Ọlọ́run gbà ń lo àkókò rẹ ṣe lè mú kó o rí gbogbo ohun rere tó ní fún ọ gbà, títí kan ayọ̀ àti àlàáfíà Rẹ̀.

Ìhùwàsí
Ọjọ́ 7
Báwo ní a ṣe lè hu ìwà tí ó yẹ nínú gbogbo ìṣẹ̀lẹ̀? Kí gan-an ni ìwà tí ó yẹ? Ètò Bíbélì ọlọ́jọ́-méje yìí wá ìdáhùn jáde nínú ìgbé-ayé àti ẹ̀kọ́ Krístì. Jẹ́ kí àwọn ìsítí ojoojúmọ́ yìí, àwọn àṣàrò àdúrà, àti àwọn ésẹ Ìwé-mímọ́ alágbára ṣe ẹ̀dà ọkàn Krístì ní inú rẹ.

Kí Ni Ète Mi? Kíkọ́ Láti Nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run àti Àwọn Ẹlòmíràn
Ọjọ́ Méje
Ye ète rẹ gẹ́gẹ́ bí ọmọlẹ́yìn Jésù: láti nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run àti láti nífẹ̀ẹ́ àwọn ẹlòmíràn. Lórí awọn ọjọ méje, a yoo tu awọn àkórí ti ìjọsìn ti ara ẹni, ìyípadà, aanu, iṣẹ, ati ìdájọ. Ìpàdé kọ̀ọ̀kan máa ń bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú àdúrà kan láti ràn ọ́ lọ́wọ́ láti ni ìfòjúsùn sórí ẹṣin ọ̀rọ̀ ọjọ́ náà, àyọkà kan tàbí méjì láti inú ìwé mímọ́, èrò kan láti inú ojú ìwòye ẹ̀kọ́ ìsìn, àti àwọn ọ̀nà láti fi sílò kí o sì dáhùn padà sí kíkà náà.