Àwọn ètò kíkà ọ̀fé àti àyọkà tó ní ṣe pẹ̀lú Luk 7:50

Ìlépa Ọkàn Ọlọ́run
Ọjọ́ 5
A ṣe àpèjúwe Ọba Dáfídì nínú Májẹ̀mú Tuntun gẹ́gẹ́ bíi ẹni bí ọkàn Ọlọ́run, tí ó túmọ̀ sí pé ọkàn rẹ ṣe déédé pẹ̀lú ti Ọlọ́run. Bí a ṣe ń kọ́ ẹ̀kọ̀ nípa ìgbésí ayé Dáfídì, ìlépa wa fún àpilẹ̀kọ yìí ni láti ṣe àyẹ̀wò àwọn ohun tí Dáfídì ṣe nínú 1 & 2 Samueli láti lè mú ọkàn wa dà bíi ti Ọlọ́run kí a sì jọ Dáfídì ní ìfarajìn àti ẹ̀mí tí ó fihàn ní gbogbo ìgbésí ayé rẹ̀.

Títẹ̀lé Jésù Olùgbèjà Wa
Ọjọ́ Méje
Oníbárà tó f'ọ́jú kan tó ń kígbe rara ní ẹ̀bá ọ̀nà, obìnrin kan tí ìgbé-ayé rẹ̀ kò tọ̀nà ní ojú mùtúmùwà tó mọ̀ọ́ṣe, òṣìṣẹ́ ìjọba kan tí gbogbo ènìyàn kórìíra – báwo ni ìkankan nínú àwọn ènìyàn yìí tí àwùjọ ti ta dànù ṣe lè ní ìrètí ìbáṣepọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run mímọ́? Pẹ̀lú àwọn ìlanilọ́yẹ̀ látinú ìwé Lúùkù nínú Bíbélì Àṣàrò fún Afrika, a ó máa tẹ̀lé Jésù bí ó ti ńṣe ìparẹ́ àwọn àlà tó wà láàárín Ọlọ́run àti àwọn tí a ti gbá sí ẹ̀gbẹ́ láwùjọ.