Àwọn ètò kíkà ọ̀fé àti àyọkà tó ní ṣe pẹ̀lú Jak 1:2

Bí ìgbé ayé ṣe yí padà: Ní àkókò Kérésìmesì
Ọjọ 5
Nínú gbogbo ìgbòkègbodò ọdún, ó ṣeéṣe kí a má kíyèsára ìdí tí a fi ń ṣe ayẹyẹ. Nínú ètò ọlọ́jọ́ márùn bíbọ̀ Oluwa yí a ó ṣe àgbéyẹ̀wò àwọn ìlérí tí ìbí Rẹ̀ mú wá sí ìmúṣẹ nípa bí a ṣe bí Jésù àti ìrètí tí a ní fún ọjọ́ iwájú. Bí a ṣe ń kẹ́kọ̀ sí í nípa ẹni tí Ọlọ́run jẹ́, a ó ṣe àwárí bí a ṣe lè máa gbé ní àkókò ìsinmi ọdún pẹ̀lú ìrètí, ìgbàgbọ́, ayọ̀, àti àlàáfíà.

Ìràpadà Ìlépa-Ọkàn
Ọjọ́ Méje
Kíni a lè ṣe nígbà tí àwọn ìlépa wa bá dàbí èyí tó jìnà réré tàbí bíi ìgbà tí a kò bá lè bá a láíláí? Lẹ́yìn tí mo borí ìlòkulò àti ìbanilọ́kànjẹ́, pẹ̀lú ẹ̀dùn ọkàn ti ìkọ̀sílẹ̀, mo ti dojúkọ ìbéèrè yìí lẹ́ẹ̀kànsi. Bóyá ò ń ní ìpèníjà ti àjálù tàbí ọ̀fọ̀, tàbí ìbànújẹ́ ti àkókò ìdádúró, ìlépa Ọlọ́run fún ìgbésí-ayé rẹ ṣì wà láàyè! Ọ̀rẹ́, àkókò tó láti lá àlá lẹ́ẹ̀kansi.

Jí Jókòó Níbi Ìdákẹ́ Rọ́rọ́: Ọjọ́ 7 Lórí Dí Dúró Sínú Ìlérí Ọlọ́run
Ọjọ́ Méje
Àwọn àkókò kan tí a gbá ìlérí Ọlọ́run mú, ṣùgbọ́n a kò rí ayé wa kí ó máa dọ́gba pẹ̀lú ìlérí náà tí Ọlọ́run fún wa. Ẹ̀wẹ̀ àkókò wà tí a bára wa ní oríta ní ìrìnàjò ayé wa, nígbàtí à ń gbára lé Ọlọ́run láti darí ipa ọ̀nà ayé wa, ṣùgbọ́n ìdákẹ́ rọ́rọ́ ni ohùn tó fọ̀ sí wa. Ètò ẹ̀kọ́ ọlọ́jọ́-7 yìí yóò sọ̀rọ̀ sí ọkàn rẹ nípa bí a ti ún rìn nínú ìfẹ́ Ọlọ́run nígbàtí ó dàbíi pé Ó dákẹ́ jẹ́.

Oswald Chambers: Ìdùnnú - Agbára Nínú Olúwa
Ọgbọ̀n ọjọ́
Sàwárí òye ti Oswald Chambers, olùkọ̀wé Sísa gbogbo ipá fún Gíga jùlọ, nínú ìṣúra èyí òye inú nípa ìdùnnú. Àwon àyọlò ọ̀rọ̀ tún tayọ nínú èkó kíkà kọ̀ọ̀kan láti Chambers nírẹ̀ẹ́pọ̀ pèlú àwon ìbéèrè fún Ijiroro tiré gan. Bí ó se mísí o àti pè o níjà pèlú òyé rè tó rorùn àti òye Bíbèlí, wa a rí ara re n fé láti lo àkókò sí i ni bibá Olórun sòrò.