1
Gẹnẹsisi 7:1
Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní
BMYO
Nígbà náà ni OLúWA wí fún Noa pé, “Wọ inú ọkọ̀ lọ ìwọ àti gbogbo ìdílé rẹ, nítorí ìwọ nìkan ni mo rí bí olódodo nínú ìran yìí.
Qhathanisa
Hlola Gẹnẹsisi 7:1
2
Gẹnẹsisi 7:24
Omi náà sì bo ilẹ̀ fún àádọ́jọ ọjọ́.
Hlola Gẹnẹsisi 7:24
3
Gẹnẹsisi 7:11
Ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kejì, tí Noa pé ọmọ ẹgbẹ̀ta (600) ọdún, ni gbogbo ìsun ibú ya, fèrèsé ìṣàn omi ọ̀run sì ṣí sílẹ̀.
Hlola Gẹnẹsisi 7:11
4
Gẹnẹsisi 7:23
Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé ni a parẹ́: ènìyàn àti ẹranko, àwọn ohun tí ń rìn nílẹ̀, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run pátápátá ló ṣègbé. Noa àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ọkọ̀ ni ó ṣẹ́kù.
Hlola Gẹnẹsisi 7:23
5
Gẹnẹsisi 7:12
Òjò àrọ̀ìrọ̀dá sì rọ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.
Hlola Gẹnẹsisi 7:12