Ìfihàn Ìfáàrà
Ìfáàrà
Ìfáàrà sí Ìwé Ìfihàn ti Johanu
Ìsọ̀rí ńlá méjì ni ìwé pàtàkì yìí ní, àkọ́kọ́ jẹ́ lẹ́tà sí ìjọ Ọlọ́run méje ní agbègbè Asia (1–3). Ìsọ̀rí kejì jẹ́ oríṣìíríṣìí ìran tó dá lórí ayé àti inúnibíni àwọn ènìyàn Ọlọ́run, ìpadàbọ̀ Kristi, ìdájọ́ ìkẹyìn, ìjọba ẹgbẹ̀rún ọdún, àti ìjọba Ọlọ́run (4–22). Àwọn ìran wọ̀nyí ń sọ nípa ìparun tó ń bọ̀ wá sórí ayé, àti ìfarahàn Jesu Kristi ní àkókò náà. Ó tún sọ nípa àwọn tí a pa nítorí ẹ̀rí Kristi àti àwọn ẹni mímọ́ tí a ṣe inúnibíni sí ní ayé. Ìran náà tẹ̀síwájú nípa ìbínú Satani sí àwọn ọmọ Ọlọ́run, ìkórè ayé, ìtẹ́ ìdájọ́ Ọlọ́run, èrè àti ìjìyà lẹ́yìn ìdájọ́ ìkẹyìn.
Ìwé yìí fi Jesu hàn bí ẹni tí a kẹ́gàn, ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run tí a pa nítorí ẹ̀ṣẹ̀ aráyé. Ìrètí gbogbo Kristiani ni pé, ní ọjọ́ kan, ohun gbogbo yóò padà bọ́ sí ipò, Ọlọ́run ni yóò jẹ́ ohun gbogbo nínú ohun gbogbo. A ó nu omijé nù, ikú, ìbànújẹ́, ẹkún àti ìrora yóò lọ pátápátá (21.4). Ọ̀rọ̀ ìtùnú yìí wà fún gbogbo Kristiani ní ìgbà gbogbo.
Kókó-ọ̀rọ̀
Ìran tí ó kọ́ wáyé 1.1-20.
Lẹ́tà méje sí àwọn ìjọ Ọlọ́run méje 2.1–3.22.
Ìran Ọlọ́run àti ọ̀dọ́-àgùntàn 4.1–5.14.
Èdìdì méje ti ìdájọ́ 6.1–8.5.
Ìpè méje ti ìdájọ́ 8.6–11.19.
Ìran ohun ti ayé àti ohun ti ọ̀run 12.1–14.20.
Ọpọ́n ìdájọ́ méje 15.1–16.21.
Ìdájọ́ àgbèrè àti Babeli 17.1–19.21.
Òpin ìran àti ìran tí ń bọ̀ 20.1–22.21.
Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:
Ìfihàn Ìfáàrà: BMYO
Ìsàmì-sí
Pín
Daako
Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀
Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní
Ẹ̀tọ́ àdàkọ © 2009, 2017 by Biblica, Inc.
A lò ó nípa ìgbàyọ̀ǹda láti ọwọ́ Bíbílíkà Inc. Ààbò lórí ẹ̀tọ́ àdàkọ yìí múlẹ̀ jákèjádò àgbáyé.
Yoruba Contemporary Bible
Copyright © 2009, 2017 by Biblica, Inc.
Used by permission of Biblica, Inc. All rights reserved worldwide.